21. Ṣùgbọ́n nígbà tí Dáfídì ọba gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi.
22. Ábúsálómù kò sì bá Ámíúnónì sọ nǹkan rere, tàbí búburú: nítorí pé Ábúsálómù kóríra Ámúnónì nítorí èyí tí ó ṣe, àní tí ó fi agbára mú Támárì àbúrò rẹ̀.
23. Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọdún méjì, Ábúsálómù sì ní olùrẹ́run àgùntàn ní Baalihásórì, èyí tí ó gbé Éfúráímù: Ábúsálómù sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba.