2 Sámúẹ́lì 11:11-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ùráyà sì wí fún Dáfídì pé, “Àpótí-ẹ̀rí, àti Ísírẹ́lì, àti Júdà jókòó nínú àgọ́; àti Jóábù olúwa mi, àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi wà ní ibùdó ní pápá: èmi ó ha lọ sí ilé mi, láti jẹ ati lati mu, àti láti bá obìnrin mi sùn? Bí ìwọ bá wà láàyè, àti bí ẹ̀mí rẹ́ si ti ń bẹ láàyè, èmi kì yóò ṣe nǹkan yìí.”

12. Dáfídì sì wí fún Ùráyà pé, “Ṣì dúró níhìn ín lónìí, lọ́la èmi ó sì jẹ́ kí ìwọ ó lọ.” Ùráyà sì dúró ní Jérúsálẹ́mù ní ọjọ́ náà, àti ijọ́ kejì.

13. Dáfídì sì pè é, ó sì jẹ, ó sì mú nítorí rẹ̀; ó sì mu kí ọtí pa á; òun sì jáde ní alẹ́ lọ sí ibùsùn rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ́ lọ sí ilé rẹ̀.

14. Ó sì ṣe ní òwúrọ̀, Dáfídì sì kọ̀wé sí Jóábù, ó fi rán Ùráyà.

15. Ó sì kọ sínú ìwé pé, “Fi Ùráyà ṣíwájú ibi tí ogun gbé le, kí ẹ sì fà sẹ́yìn, kí wọn lè kọ lù ú, kí ó sì kú.”

16. Ó sì ṣe nígbà tí Jóábù ṣe àkíyèsí ìlú náà, ó sì yan Úráyà sí ibi kàn ní ibi tí òun mọ̀ pé àwọn alágbára ọkùnrin ń bẹ níbẹ̀.

17. Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì jáde wá, wọ́n sì bá Jóábù jà: díẹ̀ sì ṣubú nínú àwọn ènìyàn náà nínú àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì, Ùráyà ará Hítì sì kú pẹ̀lú.

18. Jóábù sì ránṣẹ́ ó sì ro gbogbo nǹkan ogun náà fún Dáfídì.

19. Ó sì pàṣẹ fún ìránṣẹ́ náà pé, “Nígbà tí iwọ bá sì parí àti máa ro gbogbo nǹkan ogun náà fún ọba.

20. Bí ó bá ṣe pé, ibinú ọba bá fàru, ti òun sì wí fún ọ pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fí súnmọ́ ìlú náà láti bá wọn jà, ẹ̀yin kò mọ̀ pé wọn ó tafà láti orí odì wá.

21. Ta ni ó pa Ábímélékì ọmọ Jerubu-Bésétì? Kì í ṣe obìnrin ni ó yí òkúta ọlọ lù ú láti orí odi wá, tí ó sì kú ní Tébésì? Èé ha ti rí tí ẹ̀yín fi súnmọ́ odi náà? Ìwọ yóò sì wí fún-un pé, Ùráyà ìránṣẹ́ rẹ ará Hítì kú pẹ̀lú.’ ”

22. Ìránṣẹ́ náà sì lọ, ó sì wá, ó sì jẹ́ gbogbo iṣẹ́ tí Jóábù rán an fún Dáfídì.

2 Sámúẹ́lì 11