2 Ọba 23:18-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. “Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Ṣamáríà.

19. Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Bétélì, Jòṣíàh sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Ísírẹ́lì ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Ṣamáríà, tí ó ti mú Olúwa bínú.

20. Jòṣíáyà dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì ṣun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jérúsálẹ́mù.

21. Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé: “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”

22. Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Júdà tí ó tọ́ Ísírẹ́lì, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Ísírẹ́lì àti àwọn ọba Júdà. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.

2 Ọba 23