3. “Májẹ̀mu kan wà láàrin èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrin baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránsẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mu tí o bá Básà ọba Ísirẹ́lì dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi”
4. Bẹni-hádádì sì gbọ́ ti Ásà ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Ísírẹ́lì, wọ́n sì kọlu Íjónì, Dánì, Abeli-Máímù, àti gbogbo ilú ìsúra Náfítalì.
5. Nígbà tí Básà gbọ́ èyi, ó sì dá kíkọ́ Rámà dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
6. Nígbà náà ní ọba Ásà kó gbogbo àwọn ènìyàn Júdà jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rámà lọ èyí ti Básà ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Gébà àti Mísípà.