1 Sámúẹ́lì 20:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Bẹ́ẹ̀ ni Dáfídì sá pamọ́ sínú pápá. Nígbà tí àṣè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun sì dé, ọba sì jókòó láti jẹun.

25. Ó sì jókòó gẹ́gẹ́ bí ipò o rẹ̀ ní ibi tí ó máa ń ijòkòó lórí ìjòkó tí ó wà lẹ́gbẹ̀ ẹ́ ògiri, ní òdìkejì Jónátanì, Ábínérì sì jókòó ti Ṣọ́ọ̀lù, ṣùgbọ́n àyè Dáfídì sì ṣófo.

26. Ṣọ́ọ̀lù kò sọ nǹkan kan ní ọjọ́ náà, nítorí ó rò pé, “Nǹkan kan ti ṣẹlẹ̀ sí Dáfídì láti jẹ́ kí ó di aláìmọ́ lótìítọ́ ó jẹ́ aláìmọ́.”

27. Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì, ní ọjọ́ kejì oṣù, ààyè Dáfídì sì tún ṣófo. Nígbà náà ni Ṣọ́ọ̀lù wí fún ọmọ rẹ̀ Jónátanì pé, “Kí ni ó dé tí ọmọ Jésè kò fi wá síbi oúnjẹ, lánàá àti lónìí?”

28. Jónátanì sì dáhùn pé, “Dáfídì bẹ̀ mí tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ fún ààyè láti lọ sí Bẹ́tílẹ́hẹ́mù.

1 Sámúẹ́lì 20