1 Ọba 7:39-42 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

39. Ó sì fi ẹsẹ̀ márùn ún sí apá ọ̀tún ìhà gúṣù ilé náà àti márùn ún sí apá òsì ìhà àríwá. Ó sì gbé agbádá ńlá ka apá ọ̀tún, ní apá ìlà oòrùn sí ìdojúkọ gúṣù ilé náà.

40. Ó sì tún ṣe ìkòkò, àti ọkọ́ àti àwo kòtò.Bẹ́ẹ̀ ni Hírámù sì parí gbogbo iṣẹ́ tí ó ṣe fún ilé Olúwa fún Sólómónì ọba:

41. Àwọn ọ̀wọ̀n méjì;Ọpọ́n méjì ìparí tí ó wà lókè àwọn ọ̀wọ̀n iṣẹ́;àwọn méjì ní láti bo ọpọ́n méjì ìparí tí ń bẹ lókè àwọn ọ̀wọ̀n;

42. Irínwó (400) pómégíránátè fún iṣẹ́ àwọn méjì, ọ̀wọ́ méjì pómégíránátè fún iṣẹ́ àwọn kan láti bo àwọn ọpọ́n méjì ìparí tí ń bẹ lókè àwọn ọ̀wọ̀n;

1 Ọba 7