10. Inú Olúwa sì dùn pé Sólómónì béèrè nǹkan yìí.
11. Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún-un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀ta rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
12. èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dà bí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dà bí rẹ lẹ́yìn rẹ.
13. Ṣíwájú síi, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò bèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dà bí rẹ.