1 Ọba 2:43-46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

43. Èéṣe nígbà náà tí ìwọ kò pa ìbúra Olúwa mọ́, àti kí o sì ṣe ìgbọ́ràn sí àṣẹ tí mo pa fún ọ?”

44. Ọba sì tún wí fún Síméì pé, “Ìwọ mọ̀ ní ọkàn rẹ gbogbo búburú tí ìwọ ti ṣe sí Dáfídì baba mi. Báyìí, Olúwa yóò san gbogbo ìṣe búburú rẹ padà fún ọ.

45. Ṣùgbọ́n a ó sì bùkún fún Sólómónì ọba, ìtẹ́ Dáfídì yóò sì wà láìfòyà níwájú Olúwa títí láéláé.”

46. Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Bénáyà ọmọ Jéhóíádà, ó sì jáde lọ, ó sì kọlu Ṣíméhì, ó sì pa á.Ìjọba náà sì wá fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ Sólómónì.

1 Ọba 2