1 Ọba 18:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Èlíjà wá pé: “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Áhábù, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”

2. Bẹ́ẹ̀ ni Èlíjà lọ fi ara rẹ̀ han Áhábù.Ìyàn ńlá sì mú ní Samáríà,

3. Áhábù sì ti pe Ọbadíàh, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Ọbadíà sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.

4. Nígbà tí Jésébélì sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Ọbadíà sì mú ọgọ́rùn ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.

1 Ọba 18