1 Ọba 17:2-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Èlíjà wá pé:

3. “kúrò níhìn ín, kọjú sí ìhà ìlà oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Kérítì, tí ń bẹ níwájú Jọ́dánì.

4. Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”

5. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Kérítì, tí ń bẹ níwájú Jọ́dánì, ó sì dúró síbẹ̀.

6. Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.

7. Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.

8. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé:

1 Ọba 17