1 Ọba 16:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ṣímírì sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Áṣà, ọba Júdà, ó sì jọba ní ipò rẹ̀.

11. Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Bááṣà pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.

12. Bẹ́ẹ̀ ni Símírì pa gbogbo ilé Bááṣà run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Bááṣà nípa ọwọ́ Jéhù wòlíì:

13. nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Bááṣà àti Élà ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Ísírẹ́lì ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.

14. Ìyòókù ìṣe Élà àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Ísírẹ́lì?

1 Ọba 16