1 Ọba 11:37-43 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

37. Ṣùgbọ́n ní ti ìwọ, Èmi yóò mú ọ, ìwọ yóò sì jọba lórí ohun gbogbo tí ọkàn rẹ ń fẹ́; ìwọ yóò jọba lórí Ísírẹ́lì.

38. Bí ìwọ bá ṣe gbogbo èyí tí mo pàṣẹ fún ọ, tí o sì rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú mi nípa pípa òfin àti àṣẹ mi mọ́, bí i Dáfídì ìránṣẹ́ mi ti ṣe, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò kọ́ ilé òtítọ́ fún ọ bí èyí tí mo kọ́ fún Dáfídì, èmi yóò sì fi Ísírẹ́lì fún ọ.

39. Èmi yóò sì rẹ irú ọmọ Dáfídì sílẹ̀ nítorí èyí, ṣùgbọ́n kì í ṣe títí láé.’ ”

40. Sólómónì wá ọ̀nà láti pa Jéróbóámù, ṣùgbọ́n Jéróbóámù sá lọ sí Éjíbítì, sọ́dọ̀ Ṣísákì ọba Éjíbítì, ó sì wà níbẹ̀ títí Sólómónì fi kú.

41. Ìyòókù iṣẹ́ Sólómónì àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ọgbọ́n rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìṣe Sólómónì bí?

42. Sólómónì sì jọba ní Jérúsálẹ́mù lórí gbogbo Ísírẹ́lì ní ogójì ọdún.

43. Nígbà náà ni ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dáfídì baba rẹ̀. Réhóbóámù ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

1 Ọba 11