4. Àti pé a sìnkú rẹ̀, àti pé ó jíǹdé ní ijọ́ kẹtà gẹ́gẹ́ bí iwe mímọ́ tí wí;
5. Àti pé ó farahàn Pétérù, lẹ́yìn èyí, àwọn méjìlá
6. Lẹ́yìn èyí, ó farahàn àwọn ará tí o jú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀tà lọ lẹ́ẹ̀kan náà; ọ̀pọ̀ nínú wọn wà títí fí di ìsinsìnyìí, ṣùgbọ́n àwọn díẹ̀ ti sùn.
7. Lẹ́yìn èyí ni ó farahan Jèmísì; lẹ́yìn náà fún gbogbo àwọn Àpósítélì.
8. Àti níkẹyín gbogbo wọn ó fáráhàn mí pẹ̀lú, bí ẹni tí a bí ṣáájú àkókò rẹ̀.
9. Nítorí èmi ni ẹni tí ó kéré jùlọ nínú àwọn àpósítélì, èmi ẹni tí kò yẹ láti pè ní àpósítélì, nítorí tí mo ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run.
10. Ṣùgbọ́n nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run mo rí bí mo ti rí: oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tí a fí fún mi kò sì jẹ́ asán; ṣùgbọ́n mó ṣiṣẹ́ lọ̀pọ̀lọpọ̀ jú gbogbo wọn lọ: ṣùgbọ́n kì í ṣe èmi, bí kò ṣe oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí ó wà pẹ̀lú mi.
11. Nítorí náà ìbáà ṣe èmí tabí àwọn ni, bẹ́ẹ̀ ní àwa wàásù, bẹ́ẹ̀ ní ẹ̀yin sì gbàgbọ́
12. Ǹjẹ́ bí a bá wàásù Kírísítì pé ó tí jíǹdé kúró nínú òkú, è é há tí ṣe tí àwọn mìíràn nínú yín ti wí pé, àjíǹde òkú kò sí.
13. Ṣùgbọ́n bí àjíǹde òkú kò sí, ǹjẹ́ Kírísítì kò jíǹde.
14. Bí Kírísítì kò bá sì jíǹde, ǹjẹ́ asán ni ìwàásù wà, asán sì ni ìgbàgbọ́ yín pẹ̀lú.