1. Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Dáfídì tí a bí fún un ní Hébírónì:Àkọ́bí sì ni Ámínónì ọmọ Áhínóámù ti Jésírẹ́lì;èkejì sì ni Dáníẹ́lì ọmọ Ábígáílì ará Kárímélì;
2. Ẹ̀kẹta sì ni Ábúsálómù ọmọ Mákà ọmọbìnrin ti Táímáì ọba Gésúrì;ẹ̀kẹrin sì ni Àdóníjà ọmọ Hágítì;
3. Ẹ̀kárùnún ni Ṣéfátíyà ọmọ Ábítalì;àti ẹ̀kẹfà, Ítíréàmù, láti ọ̀dọ̀ ìyàwó Rẹ̀ Égílà.