1 Kíróníkà 29:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Wọ́n fi sílẹ̀ fún iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run, ẹgbẹ̀rún márùn-ún talẹ́ntì àti ẹgbẹ̀rin mẹ́wàá (Dáríkì) wúrà, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá talẹ́ntì fàdákà, ẹgbẹ̀rin méjìdínlógún talẹ́ntì òjíá àti ọgọ́rin ẹgbẹ̀rin talẹ́ntì irin.

8. Ẹnikẹ́ni tí ó ní òkúta iyebíye fi wọn sí ilé ìṣúra ilé Ọlọ́run ní ìhámọ́ Jéhíélì ará Géríṣónì.

9. Àwọn ènìyàn láyọ̀ nínú ìṣesí àtọkànwá fi sílẹ̀ àwọn olórí wọn, nítorí tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ọ̀fẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn sí Olúwa. Dáfídì ọba pẹ̀lú yọ̀ gidigidi.

10. Dáfídì yin Olúwa níwájú gbogbo àwọn tí ó péjọ, wí pé,“Ìyìn ni fún Ọ, Olúwa,Ọlọ́run baba a wa Ísírẹ́lì,láé àti láéláé.

11. Tìrẹ Olúwa ni títóbi àti agbára pẹ̀lú ìyìnàti ọlá ńlá àti dídán,nítorí tí gbogbo nǹkan ní ọ̀run àti ayé jẹ́ tìrẹ.Tìrẹ Olúwa ni ìjọba;a gbé ọ ga gẹ́gẹ́ bí orí lórí ohun gbogbo.

1 Kíróníkà 29