1 Kíróníkà 2:2-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Dánì, Jóṣẹ́fù, Bẹ́ńjámínì; Náfítanì, Gádì: àti Áṣérì.

3. Àwọn ọmọ Júdà:Érì, Ónánì àti Ṣélà, àwọn mẹ́tẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kénánì, ọmọbìnrin Súà Érì àkọ́bí Júdà, ó sì burú ní ojú Olúwa; Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.

4. Támárì, aya ọmọbìnrin Júdà, ó sì bí Fárésì àti Ṣérà sì ní ọmọ márùn ún ní àpapọ̀

5. Àwọn ọmọ Fárésì:Hésírónì àti Hámúlù.

6. Àwọn ọmọ Ṣérà:Ṣímírì, Étanì, Hémánì, Kálíkólì àti Darà, gbogbo wọn jẹ́ márùn ún.

7. Àwọn ọmọ Kárímì:Ákárì, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Ísírẹ́lì nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.

8. Àwọn ọmọ Étanì:Áṣáríyà

9. Àwọn ọmọ tí a bí fún Hésírónì ni:Jéráhímélì, Rámù àti Kélẹ́bù.

10. Rámù sì ni babaÁmínádábù, àti Ámínádábù baba Náṣónì olórí àwọn ènìyàn Júdà.

11. Náṣónì sì ni baba Sálímà, Sálímà ni baba Bóásì,

12. Bóásì baba Óbédì àti Óbédì baba Jésè.

13. Jésè sì ni BabaÉlíábù àkọ́bí Rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kẹjì sì ni Ábínádábù, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣíméà,

14. Ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Nàtaníẹ́lì, ẹlẹ́ẹ̀káàrùn-ún Rádáì,

15. ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Ósémù àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dáfídì.

16. Àwọn arábìnrin wọn ni Ṣérúà àti Ábígáílì. Àwọn ọmọ mẹ́ta Ṣérúà ni Ábíṣáì, Jóábù àti Ásáélì.

17. Ábígáílì ni ìyá Ámásà, ẹni tí baba Rẹ̀ sì jẹ́ Jétérì ará Íṣímáẹ́lì.

18. Kélẹ́bù ọmọ Hésírónì ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó Rẹ̀ Ásúbà (láti ọ̀dọ̀ Jéríótù). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Rẹ̀: Jéṣérì, Ṣóbábù àti Árídónì.

19. Nígbà tí Ásúbà sì kú, Kélẹ́bù sì fẹ́ Éfúrátì ní aya, ẹni tí ó bí Húrì fún un.

1 Kíróníkà 2