1 Kíróníkà 10:6-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Bẹ́ẹ̀ ni Ṣọ́ọ̀lù àti ọmọ Rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta kú gbogbo ilé Rẹ̀ sì kú lápapọ̀.

7. Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ rí wí pé àwọn ọmọ ogun ti sálọ àti pé Ṣọ́ọ̀lù àti àwọn ọmọ Rẹ̀ ti kú wọ́n kọ àwọn ìlú wọn sílẹ̀, wọ́n sì sálọ. Àwọn ará Fílístínì wá, wọ́n sì gba ipò wọn.

8. Ní ọjọ́ kejì, Nígbà tí àwọn ará Fílístínì wá láti kó okú, wọ́n rí Ṣọ́ọ̀lù àti àwọn ọmọ Rẹ̀ tí wọ́n ṣubú sórí òkè Gílíbóà.

9. Wọ́n bọ́ ọ láọ (Stripped), wọ́n sì gbé orí Rẹ̀ àti ìhámọ́ra Rẹ̀. Wọ́n sì rán ìránṣẹ́ lọ kákiri ilẹ̀ Àwọn ará Fílístínì láti kéde ìròyìn náà láàrin àwọn òrìṣà wọn àti àwọn ènìyàn wọn.

1 Kíróníkà 10