1 Kíróníkà 1:47-54 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

47. Nígbà tí Hádádì sì kú, Ṣámílà láti Másírékà, ó sì jọba ní ipò Rẹ̀

48. Nígbà tí Ṣámílà sì kú, Ṣáúlì láti Réhóbótì lórí odò sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀

49. Nígbà tí Ṣáúlì sì kú, Báli-hánánì, ọmọ Ákíbórì sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀.

50. Nígbà tí Báli-hánánì sì kú, Hádádì sì di ọba nípò Rẹ̀. Orúkọ ìlú Rẹ̀ sì ni Páì; àti orúkọ ìyàwó sì ni Méhélábélì ọmọbìnrin Métírédì, ọmọbìnrin Mésíhábù.

51. Hádádì sì kú pẹ̀lú.Àwọn olórí Édómù ni:Tímínà, Álífà, Jététì

52. Óhólíbámà, Élà, Pínónì.

53. Kénásì, Témánì, Mísárì,

54. Mágádíẹ́lì àti Ìrámù. Àwọn wọ̀nyí ni Olórí Édómù.

1 Kíróníkà 1